Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àwọn Hébérù 13:1-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Kí ìfẹ́ ará o wà títí.

2. Ẹ má ṣe gbàgbé láti máa ṣe àléjò; nítorí pé nípa bẹ́ẹ̀ ni àwọn ẹlòmíràn ṣe àwọn áńgẹ́lì ní àlejò láìmọ̀.

3. Ẹ máa rántí àwọn òǹdè bí ẹni tí a dè pẹ̀lú wọn, àti àwọn tí a ń pọn lójú bí ẹ̀yin tikarayin pẹ̀lú tí ń bẹ nínú ara.

4. Kí ìgbéyàwó lọ́lá láàrin gbogbo ènìyàn, kí àkéte si jẹ́ aláìléérí: Nítorí àwọn àgbérè àti àwọn panṣágà ni Ọlọ́run yóò dá lẹ̀jọ́.

5. Ki ọkàn yín má ṣe fà sí ìfẹ́ owó, ki ohun tí ẹ ní tó yin; nítorí oun tìkararẹ̀ ti wí pé,“Èmi kò jẹ fi ọ́ sílẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni èmi kò jẹ kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”

6. Nítorí náà ni àwa ṣe ń fi ìgboyà wí pé,“Olúwa ni oluranlọ́wọ́ mi, èmi kì yóò bẹ̀rù;kínni ènìyàn lè ṣe sí mi?”

7. Ẹ máa rántí àwọn ti wọn jẹ́ aṣáájú yín, ti wọn ti sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fún yín; kí ẹ máa ro òpin ìwà-ayé wọn, kí ẹ sì máa ṣe àfarawé ìgbàgbọ́ wọn.

8. Jésù Kírísítì ọ̀kan náà ni lánà, àti lóní, àti títí láé.

9. Ẹ má ṣe jẹ́ kí a fi onírúurú àti àjèjì ẹ̀kọ́ gbá yin kiri. Nítorí ó dára kí a mú yin lọ́kàn le nípa oore-ọ̀fẹ́, kì í ṣe nípa oúnjẹ nínú èyí tí àwọn tí ó ti rìn nínú wọn kò ní èrè.

10. Àwa ní pẹpẹ kan, níbi èyí tí àwọn ti ń sin àgọ́ kò ni agbára láti máa jẹ.

Ka pipe ipin Àwọn Hébérù 13