Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àwọn Hébérù 11:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ǹjẹ́ ìgbàgbọ́ ní ìdánilójú ohun tí o ń réti, ìjeri ohun tí a kò rí.

2. Nítorí nínú rẹ ni àwọn alàgbà (atijọ́) ní ẹ̀rí rere.

3. Nípa ìgbàgbọ́ ni a mọ̀ pé a ti dá ayé nípa ọ̀rọ̀ Ọlọ́run; nítorí náà kì í ṣe ohun tí o hàn ni a fi dá ohun tí a ń ri.

4. Nípa ìgbàgbọ́ ní Ábélì rú ẹbọ sí Ọlọ́run tí ó sàn ju ti Káínì lọ, nípa èyí tí a jẹ̀rí rẹ̀ pe olódodo ni, Ọlọ́run sí ń jẹ́ri ẹ̀bùn rẹ̀: Àti nípa rẹ̀ náà, bí o ti jẹ́ pé o ti kú, síbẹ̀ o ń fọhùn.

5. Nípa ìgbàgbọ́ni a sì Énókù nípò padà kí o má ṣe rí ikú; a kò sí rí i, nítorí ti Ọlọ́run ṣi i nípò padà: nítorí ṣaáju ìsìpo padà rẹ̀, a jẹ́ri yìí si i pé o wu Ọlọ́run.

Ka pipe ipin Àwọn Hébérù 11