Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Àwọn Hébérù 10:12-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Ṣùgbọ́n òun, lẹ̀yìn ìgbà tí o ti rú ẹbọ kan fún ẹ̀ṣẹ̀ títí láé, o jòkòó lọ́wọ́ ọ̀tún Ọlọ́run;

13. Láti ìgbà náà, ó rétí títí a o fi àwọn ọ̀ta rẹ̀ ṣe àpótí itísẹ̀ rẹ̀.

14. Nítorí nípa ẹbọ kan a ti mú àwọn tí a sọ di mímọ́ pé títí láé.

15. Ẹ̀mí mímọ́ sì ń jẹri fún wa pẹ̀lú: Nítorí lẹ̀yìn tí ó wí pé,

16. “Èyí ni májẹ̀mú ti èmi o ba wọn dálẹ́hìn àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, ni Olúwa wí,èmi o fi òfin mi sí wọn ní ọkàn,inú wọn pẹ̀lú ni èmi o sì kọ wọn sí.”

17. “Ẹ̀ṣẹ̀ wọn àti àìṣedéédéwọn lèmi kì yóò sì rántí mọ́.”

18. Ṣùgbọ́n níbi tí ìmukúrò ìwọ̀nyí bá gbé wà, ìrubọ fún ẹ̀ṣẹ̀ kò sí mọ́.

19. Ará, ǹjẹ́ bí a ti ní ìgboyà láti wọ inú ibi mímọ́ nípasẹ̀ ẹ̀jẹ̀ Jésù,

20. Nípa ọ̀nà títún àti ààyè, tí o yà sí mímọ́ fún wa, àti láti kọja aṣọ ìkelé èyí yìí ní, ara rẹ̀;

21. Àti bí a ti ni àlùfáà gíga lórí ilé Ọlọ́run;

22. Ẹ jẹ́ kí a fi òtítọ́ ọkàn súnmọ́ tòòsí ni ẹ̀kún ìgbàgbọ́, kí a sì wẹ ọkàn wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀rí ọkan búburú, kí a sì fi omi mímọ́ wẹ ara wa nù.

23. Ẹ jẹ́ kí a di ìjẹ́wọ́ ìreti wa mu ṣinṣin ni àìsiyèméjì; (nítorí pé olóòtọ́ ní ẹni tí o ṣe ìlérí).

24. Ẹ jẹ́ kí a yẹ ara wa wò láti ru ara wa sí ìfẹ́ àti sí iṣẹ́ rere:

25. Kí a ma máa kọ ìpejọpọ̀ ara wa sílẹ̀, gẹ́gẹ́ bi àṣà àwọn ẹlòmíràn; ṣùgbọ́n kí a máa gba ara ẹni niyànjú pẹ̀lúpẹ̀lú bí ẹ̀yin ti rí i pé ọjọ́ náà ń súnmọ etílé.

26. Nítorí bí àwa ba mọ̀ọ́mọ̀ dẹ́sẹ̀ lẹ̀yìn ìgbà tí àwa bá ti gba ìmọ̀ òtítọ́ kò tún sí ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ mọ́.

27. Bí kò ṣe ìrètí ìdájọ́ tí ó ba ní lẹ̀rù, àti ti ìbínú ti o múná, tí yóò pa àwọn ọ̀ta run.

Ka pipe ipin Àwọn Hébérù 10