Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kọ́ríńtì 6:5-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. nípa nínà, nínú túbú, nínú ìrúkèrúdò, nínú iṣẹ́ àṣekára, nínú àìṣan, nínú ìgbààwẹ̀.

6. Nínú ìwà mímọ̀, nínú ìmọ̀, nínú ìpamọ́ra, nínú ìṣeun, nínú Ẹ̀mi Mímọ̀, nínú ìfẹ́ àìṣẹ̀tàn.

7. Nínú ọ̀rọ̀ òtítọ́, nínú agbára Ọlọ́run, nínú ìhámọ́ra òdodo ní apá ọ̀tún àti ní apa òsì.

8. Nípa ọlá àti ẹ̀gàn, nípa ìyìn búburú àti ìyìn rere: bí ẹlẹ́tàn, ṣùgbọ́n a já sí ólóòótọ́,

9. bí ẹni tí a kò mọ̀, ṣùgbọ́n a mọ̀ wá dájúdájú; bí ẹni tí ń kú lọ, ṣùgbọ́n a si wà láàyè; bí ẹni tí a nà, ṣùgbọ́n a kò sì pa wá,

10. bí ẹni tí ó kún fún ìbànújẹ́, ṣùgbọ́n àwa ń yọ̀ nígbà gbogbo; bí talákà, ṣùgbọ́n àwa ń sọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ dí ọlọ́rọ̀; bí ẹni tí kò ní nǹkan, ṣùgbọ́n àwa ni ohun gbogbo.

11. Ẹ̀yin ará Kọ́ríńtì, a ti bá yín sọ òtítọ́ ọ̀rọ̀, a ṣí ọkàn wa payá sí yín.

12. A kò ni yín lára nítorí wa, ṣùgbọ́n a ni yín lára nítorí ìfẹ́ ọkàn ẹ̀yin fúnra yín.

Ka pipe ipin 2 Kọ́ríńtì 6