16. Ìrẹ́pọ̀ kín ni tẹ́ḿpìlì Ọlọ́run ní pẹ̀lú òrìṣà? Nítorí ẹ̀yin ní tẹ́ḿpìlì Ọlọ́run alààyè; gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti wí pé, “Èmi á gbé inú wọn, èmi o sì máa rìn láàárin wọn; èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, wọn yóò sì jẹ́ ènìyàn mi.”
17. “Nítorí náà ẹ jáde kúrò láàárin wọn,kí ẹ sì yá ara yín si ọ̀tọ̀,ni Olúwa wí.Ki ẹ má ṣe fi ọwọ kan ohun àìmọ́;Èmi ó sì gbà yín.”
18. “Èmi o sì jẹ́ Baba fún yín,Ẹ̀yin ó sì jẹ́ ọmọkùnrin mi àti ọmọbìnrin mi!ní Olúwa Olódùmarè wí.”