Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kọ́ríńtì 6:15-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ìrẹ́pọ̀ kín ni Kírísítì ní pẹ̀lú Bélíàlì? Tàbí ìpín wó ni ẹni tí ó gbàgbọ́ ní pẹ̀lú aláìgbàgbọ́?

16. Ìrẹ́pọ̀ kín ni tẹ́ḿpìlì Ọlọ́run ní pẹ̀lú òrìṣà? Nítorí ẹ̀yin ní tẹ́ḿpìlì Ọlọ́run alààyè; gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti wí pé, “Èmi á gbé inú wọn, èmi o sì máa rìn láàárin wọn; èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, wọn yóò sì jẹ́ ènìyàn mi.”

17. “Nítorí náà ẹ jáde kúrò láàárin wọn,kí ẹ sì yá ara yín si ọ̀tọ̀,ni Olúwa wí.Ki ẹ má ṣe fi ọwọ kan ohun àìmọ́;Èmi ó sì gbà yín.”

18. “Èmi o sì jẹ́ Baba fún yín,Ẹ̀yin ó sì jẹ́ ọmọkùnrin mi àti ọmọbìnrin mi!ní Olúwa Olódùmarè wí.”

Ka pipe ipin 2 Kọ́ríńtì 6