Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kọ́ríńtì 12:12-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Ohun kan tí ó ṣe àmì àpósítélì, iṣẹ́ ìyanu and iṣẹ́ agbára ní won ṣe ní àárin yín pẹ̀lú sùúrù tó ga.

13. Nítorí nínú kín ni ohun tí ẹ̀yin ṣe rẹ̀yìn sí ìjọ mìíràn, bí kò ṣe ní ti pé èmi fúnra mi kó jẹ́ oníyọnú fún yín? Ẹ dárí àṣìṣe yìí jì mí.

14. Kíyèsí i, ìgbà kẹta yìí ni mo múra tan láti tọ̀ yín wá: èmi kì yóò sì jẹ́ oníyọnu fún yín nítorí tí èmi kò wá nǹkan yín, bí kò ṣe ẹ̀yin fúnra yín; nítorí tí kò tọ́ fún àwọn ọmọ láti máa to ìṣúra jọ fún àwọn òbí wọn, bí kò se àwọn òbí fún àwọn ọmọ wọn.

15. Èmi ó sì fi ayọ̀ ná ohun gbogbo tí mo bá ní, èmi ó sì ná ara mi fún ọkàn yín nítòótọ́; bí mo bá fẹ́ yín lọ́pọ̀lọpọ̀, ó há tọ́ kí ẹ̀yin kí ó fẹ́ràn mi díẹ̀ bí?

16. Ṣùgbọ́n ó dára bẹ́ẹ̀ tí èmi kò dẹ́rúbà yín: ṣùgbọ́n bí ọlọ́gbọ́n ènìyàn, èmi ń fí ọwọ́ ẹ̀rọ̀ mú yín.

17. Èmi há rẹ́ yín jẹ nípa ẹnikẹ́ni nínú àwọn tí mo rán sí yín bi?

18. Mo bẹ Títù, mo sì rán arákùnrin kan pẹ̀lú rẹ̀; Títù há rẹ́ yín jẹ bí? Nípa ẹ̀mi kan náà kọ́ àwa rìn bí? Ọ̀nà kan náà kọ́ àwa tọ̀ bí?

Ka pipe ipin 2 Kọ́ríńtì 12