Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Tímótíù 4:7-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Ṣùgbọ́n kọ ọ̀rọ̀ asán àti ìtàn àwọn àgbà obìnrin, sì máa tọ́ ara rẹ sí ìwà-bí-Ọlọ́run.

8. Nítorí ṣíṣe eré-ìdárayá ni èrè fún ohun díẹ̀, ṣùgbọ́n ìwá-bí-Ọlọ́run ni èrè fún ohun gbogbo, ó ní ìlérí ti igbé-ayé ìṣinṣinyìí àti ti èyí tí ń bọ̀,

9. Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ náà, ó sì yẹ fún ìtẹ̀wọ́gbà gbogbo.

10. Nítorí fún èyí ni àwa ń ṣe làálàá tí a sì ń jìjàkadì, nítorí àwá ní ìrèti nínú Ọlọ́run alààyè, ẹni tí í ṣe Olùgbàlà gbogbo ènìyàn, pẹ̀lúpẹ̀lú ti àwọn ti ó gbàgbọ́.

11. Nǹkan wọ̀nyí ni kí ó máa paláṣẹ̀ kí ó máa kọ́ni.

12. Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni gan èrè rẹ; ṣùgbọ́n kì ìwọ jẹ́ àpẹẹrẹ fún àwọn tí ó gbàgbọ́, nínú ọ̀rọ̀, nínú ìwàhíhù, nínú ìfẹ́, nínú ẹ̀mí, nínú ìgbàgbọ́, nínú ìwà mímọ́,

13. Títí èmi ó fi dé, máa fiyèsí kíkàwé àti ìgbani-níyànjú àti ìkọ́ni.

14. Má ṣe àìnání ẹ̀bùn tí ń bẹ lára rẹ, èyí tí a fi fún ọ nípa ìsọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú ìgbọ́wọ́lé àwọn alàgbà.

15. Má a fiyèsí nǹkan wọ̀nyí; fi ara rẹ fún wọn pátápátá; kí ìlọṣíwájú rẹ lè hàn gbangba fún gbogbo ènìyàn.

16. Má a ṣe ìtọ́jú ará rẹ àti ẹ̀kọ́ rẹ; máa dúró láiyẹsẹ̀ nínú nǹkan wọ̀nyí; nítorí ní ṣíṣe èyí, ìwọ ó gba ara rẹ àti tí àwọn ti ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ là.

Ka pipe ipin 1 Tímótíù 4