Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Tẹsalóníkà 5:2-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. nítorí ẹ̀yin pàápàá mọ̀ wí pé ọjọ́ Olúwa yóò wàá bí olè lóru.

3. Ní àkókò gan an tí àwọn ènìyàn yóò máa wí pé, “Àláfíà àti àbò,” nígbà náà ni ìparun òjijì yóò dé sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ìrọbí obìnrin tí ó lóyún, wọn kò sí rí ibi ààbò láti sá sí.

4. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ará, kò sí nínú òkùnkùn nípa nǹkan wọ̀nyí tí ọjọ́ Olúwa yóò fi dé bá yín bí olè.

5. Nítorí gbogbo yín ni ọmọ ìmọ́lẹ̀ àti ọmọ ọ̀sán gangan. Ẹ kì í ṣe tí òru tàbí tí òkùnkùn mọ́.

6. Nítorí náà, ẹ kíyèsára yín kí ẹ má ṣe sùn bí àwọn ẹlòmíràn. Ẹ máa sọ́nà kí ẹ sì máa pa ara yín mọ́.

7. Nítorí àwọn tí owọ́n ń sùn, a máa sùn ní òru, àwọn ẹni tí ń mu àmupara, a máa mú un ní òru.

8. Ṣùgbọ́ń àwa jẹ́ ti ìmọ́lẹ̀, ẹ jẹ́ kí a pa ara wa mọ́, ní gbígbé ìgbàgbọ́ wọ̀ àti ìfẹ́ bí awo igbaaya ni òru àti ìrètí ìgbàlà bí asìborí.

Ka pipe ipin 1 Tẹsalóníkà 5