Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Pétérù 5:6-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Nítorí náà, ẹ rẹ ara yin sílẹ̀ lábẹ́ ọwọ́ agbára Ọlọ́run, kí òun lè gbe yín ga lákòókò.

7. Ẹ máa kó gbogbo àníyàn yín lé e; nítorí tí òun ń ṣe ìtọ́jú yín.

8. Ẹ máa wà ni àìrékọjá, ẹ máa ṣọ́ra; nítorí Èṣù ọ̀ta yín, bí kínnìún tí ń ke ramúramù, o ń rìn káàkiri, ó ń wa ẹni tí yóò pajẹ.

9. Ẹ kọ ojú ìjà sí i pẹ̀lú ìdúró ṣinṣin nínú ìgbàgbọ́, bí ẹ̀yin ti mọ̀ pé ìyà kan-náà ni àwọn ará yín tí ń bẹ nínú ayé ń jẹ.

10. Ọlọ́run oore-ọ̀fẹ́ gbogbo, tí ó ti pè yín sínú ògo rẹ̀ tí kò nípẹ̀kun nínú Kírísítì Jésù, nígbà tí ẹ̀yin bá ti jìyà díẹ̀, òun tìkararẹ̀, yóò sì ṣe yín ní àṣepé, yóò fi ẹsẹ̀ yín múlẹ̀, yóò fún yín lágbára, yóò fi ìdí yín kalẹ̀.

11. Tírẹ̀ ni ògo àti agbára títí láé (Àmín)

Ka pipe ipin 1 Pétérù 5