Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Pétérù 2:21-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Sí èyí ni a pè yín: nítorí Kírísítì pẹ̀lú jìyà fún-un yin, ó fi àpẹẹrẹ sílẹ̀ fún-un yín, kí ẹ̀yin lè máa tọ ipaṣẹ̀ rẹ̀:

22. “Òun kò dẹ́ṣẹ̀ kankan,bẹ́ẹ̀ sì ni, a kò rí ẹ̀tàn kan lẹ́nu rẹ̀”

23. Ẹni, nígbà tí a kẹ́gàn rẹ̀, tí kò sì padà kẹ́gàn; nígbà tí ó jìyà tí kò sì halẹ̀; ṣùgbọ́n ó fi ọ̀ràn rẹ̀ lé ẹni ti ń ṣe ìdájọ́ òdodo lọ́wọ́.

24. Ẹni tí òun tìkararẹ̀ fi ara rẹ̀ ru ẹ̀ṣẹ̀ wa lórí igi, pé kí àwa lè di òkú sí ẹ̀ṣẹ̀ ki a sì di ààyè sí òdodo: nípa ìjìyà ẹni tí ó mú yín láradá.

25. Nítorí tí ẹ̀yin ń ṣáko lọ bí àgùntàn, ṣùgbọ́n nísinsinyìí ẹ̀yin ti padà sí ọ̀dọ̀ olùsọ́-àgùntàn àti bíṣọ́ọ̀bù ọkàn yín.

Ka pipe ipin 1 Pétérù 2