Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Pétérù 2:18-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Ẹ̀yin ọmọ-ọdọ, ẹ máa tẹríba fún àwọn ọ̀gá yín pẹ̀lú ìbẹ̀rù gbogbo, kì í ṣe fún àwọn ẹni rere àti oníwà tútù nìkan, ṣùgbọ́n fún àwọn òǹrorò pẹ̀lú.

19. Nítorí pé èyí ní ìgbóríyìn fún, bí ènìyàn bá fi oara da ìrora, ìjìyà lọ́nà àìtọ́, nítorí ọkàn rere sí Ọlọ́run.

20. Ṣùgbọ́n ògo kínni ó jẹ́, nígbà tí ẹ ba sẹ̀ tí a sì lù yín, bí ẹ bá fi sùúrù gbà á? Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin bá ń ṣe rere tí ẹ sì ń jìyà, bí ẹ bá fi sùúrù gbà á, èyí ní ìgbóríyìn-fún lọ́dọ̀ Ọlọ́run.

21. Sí èyí ni a pè yín: nítorí Kírísítì pẹ̀lú jìyà fún-un yin, ó fi àpẹẹrẹ sílẹ̀ fún-un yín, kí ẹ̀yin lè máa tọ ipaṣẹ̀ rẹ̀:

22. “Òun kò dẹ́ṣẹ̀ kankan,bẹ́ẹ̀ sì ni, a kò rí ẹ̀tàn kan lẹ́nu rẹ̀”

Ka pipe ipin 1 Pétérù 2