Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Pétérù 2:14-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Tàbí fún àwọn baálẹ̀, fún àwọn tí a rán láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ fún ìgbẹ̀san lára àwọn tí ń ṣe búburú, àti fún ìyìn àwọn tí ń ṣe rere.

15. Ìfẹ́ Ọlọ́run sá ni èyí pé, ní rere í ṣe, kí ẹ lè dẹ́kun ọ̀rọ̀ àìmọ̀kan òmùgọ̀ ènìyàn.

16. Ẹ máa gbé gẹ́gẹ́ bí ẹni òmìnira, ṣùgbọ́n ẹ maṣe lo òmìnira yín láti bo ibi mọ́lẹ̀; ṣùgbọ́n kí ẹ gbé gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ Ọlọ́run.

17. Ẹ bọ̀wọ̀ fún gbogbo ènìyàn, ẹ fẹ àwọn ará, ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run, ẹ bọ̀wọ̀ fún ọba.

18. Ẹ̀yin ọmọ-ọdọ, ẹ máa tẹríba fún àwọn ọ̀gá yín pẹ̀lú ìbẹ̀rù gbogbo, kì í ṣe fún àwọn ẹni rere àti oníwà tútù nìkan, ṣùgbọ́n fún àwọn òǹrorò pẹ̀lú.

19. Nítorí pé èyí ní ìgbóríyìn fún, bí ènìyàn bá fi oara da ìrora, ìjìyà lọ́nà àìtọ́, nítorí ọkàn rere sí Ọlọ́run.

20. Ṣùgbọ́n ògo kínni ó jẹ́, nígbà tí ẹ ba sẹ̀ tí a sì lù yín, bí ẹ bá fi sùúrù gbà á? Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin bá ń ṣe rere tí ẹ sì ń jìyà, bí ẹ bá fi sùúrù gbà á, èyí ní ìgbóríyìn-fún lọ́dọ̀ Ọlọ́run.

21. Sí èyí ni a pè yín: nítorí Kírísítì pẹ̀lú jìyà fún-un yin, ó fi àpẹẹrẹ sílẹ̀ fún-un yín, kí ẹ̀yin lè máa tọ ipaṣẹ̀ rẹ̀:

22. “Òun kò dẹ́ṣẹ̀ kankan,bẹ́ẹ̀ sì ni, a kò rí ẹ̀tàn kan lẹ́nu rẹ̀”

23. Ẹni, nígbà tí a kẹ́gàn rẹ̀, tí kò sì padà kẹ́gàn; nígbà tí ó jìyà tí kò sì halẹ̀; ṣùgbọ́n ó fi ọ̀ràn rẹ̀ lé ẹni ti ń ṣe ìdájọ́ òdodo lọ́wọ́.

24. Ẹni tí òun tìkararẹ̀ fi ara rẹ̀ ru ẹ̀ṣẹ̀ wa lórí igi, pé kí àwa lè di òkú sí ẹ̀ṣẹ̀ ki a sì di ààyè sí òdodo: nípa ìjìyà ẹni tí ó mú yín láradá.

25. Nítorí tí ẹ̀yin ń ṣáko lọ bí àgùntàn, ṣùgbọ́n nísinsinyìí ẹ̀yin ti padà sí ọ̀dọ̀ olùsọ́-àgùntàn àti bíṣọ́ọ̀bù ọkàn yín.

Ka pipe ipin 1 Pétérù 2