Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Pétérù 2:1-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nítorí náà, ẹ fi àrankan gbogbo sílẹ̀ ni apákan, àti ẹ̀tàn gbogbo, àti àgàbàgebè, àti ìlára, àti sísọ ọ̀rọ̀ buburú gbogbo.

2. Bí ọmọ ọwọ́ titun, kí ẹ máa fẹ́ wàrà ti Ẹ̀mí, èyí tí kò lẹ́tàn, kí ẹ̀yín lè máa tipasẹ̀ rẹ̀ dàgbà sí ìgbàlà.

3. nísinsìnyìí tí ẹ̀yín ti tọ́ ọ wò pé rere ni Olúwa

4. Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti tọ̀ ọ́ wá, òkúta ààyè náà, èyí ti àwọn ènìyàn kọ̀ sílẹ̀ ṣùgbọ́n tí Ọlọ́run yàn, òkúta iyebíye.

5. Ẹ̀yin pẹ̀lú, bí òkúta ààyè, ni a kọ́ ní ilé ẹ̀mí, àlùfáà mímọ́, láti máa rú ẹbọ ẹ̀mí, tí i ṣe ìtẹ́wọ́gbà lọ́dọ̀ Ọlọ́run nípa Jésù Kírísítì.

6. Nítorí nínú ìwé mímọ́, ó wí pe:“Kìyèsi i, mo fi pàtàkì òkúta ìgún-ilẹ̀ àṣàyàn,iyebíye, lélẹ̀ ni Síónì:ẹni tí ó bá sì gbà á gbọ́ojú kì yóò tì í.”

7. Báyìí fún ẹ̀yin ti ẹ gbà á gbọ́, ó ṣe iyebíye; ṣùgbọ́n fún àwọn tí kò gbà á gbọ́,“Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀ sílẹ̀,òun ni ó di pàtàkì ìgún-ilé,”

8. àti pẹ̀lú,“Òkúta ìdìgbòlù,àti àpáta ìkọ̀sẹ̀.”Nítorí wọn kọsẹ̀ nípa ṣíṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ náà, sínú èyí tí a gbé yàn wọ́n sí pẹ̀lú.

9. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni ìran tí a yàn Olu àlùfáà, Orílẹ̀ èdè mímọ́, ènìyàn ọ̀tọ̀ ki ẹ̀yin lè fi ọla ń lá ẹni tí ó pè yín jáde kúrò nínú òkùnkùn sínú ìmọ́lẹ̀ ìyanu rẹ̀ hàn:

10. Ẹ̀yin tí kì í ṣe ènìyàn nígbà kan rí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ̀yin ti di ènìyàn Ọlọ́run, ẹ̀yin tí kò rí àánú gbà rí, ṣùgbọ́n nísinsinyìí, ẹ ti rí àánú gbà.

Ka pipe ipin 1 Pétérù 2