Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Pétérù 1:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Pétérù, Àpósítélì Jésù Kírísítì,Sí àwọn àyànfẹ́ Ọlọ́run, ti wọ́n ń ṣe àtìpó ní àgbáyé, ti wọn tú káàkiri sí Pọ́ńtù, Gálátíà, Kápádókíà, Ésíà, àti Bítíníà,

2. àwọn ẹni tí a ti yàn gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀ tẹ́lẹ̀ Ọlọ́run Baba, nípa ìsọdimímọ́ Ẹ̀mí, sí ìgbọ́ràn àti ìbùwọ́n ẹ̀jẹ̀ Jésù Kírísítì:Kí oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà máa bí sì fún yín.

3. Ìyìn yẹ Ọlọ́run àti Baba Jésù Kírísítì Olúwa wa! Ẹni tí ó tún wa bí gẹ́gẹ́ bí àánú ńlárẹ̀ sínú ìrètí ààyè nípa àjíǹde Jésù Kírísítì kúrò nínú òkú,

4. àti sínú ogún àìdíbàjẹ́, àti àìlábàwọ́n, àti èyí tí kì í sá, tí a ti fi pamọ́ ni ọ̀run dè yin,

Ka pipe ipin 1 Pétérù 1