Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 9:15-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ṣíbẹ̀síbẹ̀ n kò ì tí ì lo iru àwọn ẹ̀tọ́ wọ̀nyí rí. Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì kọ lẹ́tà yìí láti fi sọ fún un yín pé, mo fẹ́ bẹ̀rẹ̀ sí í gbà irú nǹkan bẹ̀ẹ́ lọ́wọ́ yín. Kí a sọ òtítọ́, ó sàn fún mi láti kú sínú ebi ju pé kí n sọ ayọ̀ tí mo ní láti wàásù nù.

16. Nítorí pé bí mo ti ń wàásù ìyìn rere, kì í se ohun tí mo lè máa sogo lè. Èmi kò tilẹ̀ le è ṣe é ní, kí a tilẹ̀ sọ pé mo fẹ́ kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Ègbé ni fún mi tí mo bá kọ̀ láti wàásù ìyìn rere.

17. Tó bá jẹ́ pé mò ń wàásù tinútinú mi, nígbà náà Olúwa ní ẹ̀bùn pàtàkì fún mi, ṣùgbọ́n tí ń kò bá ṣe é tinútinú mi, mo ṣe àsìlò ìdanilójú tí a ní nínú mi.

18. Ní irú ipò báyìí, kí ni ẹ rò pé èrè mi ni láti jẹ́? Èrè mi ní àgbàyanu ayọ̀ tí mo ń rí gbà nípa ìwàásù ìyìn rere láèná ẹnikẹ́ni lówó, láìbéèrè ẹ̀tọ́ mi lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni.

19. Bí mo ti jẹ́ òmìnira tí ń kò sì dara pọ̀ mọ́ ẹnikẹ́ni, mo sọ ara mi di ẹrú lọ́dọ̀ gbogbo ènìyàn, láti lè jèrè ọ̀pọ̀lọ́pọ̀ sí i.

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 9