Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 7:15-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin tí i ṣe aláìgbàgbọ́ náà bá fẹ́ láti lọ, jẹ́ kí ó máa lọ. Onígbàgbọ́ ọkùnrin tàbí obìnrin náà kò sí lábẹ́ idè mọ́; Ọlọ́run ti pè wá láti gbé ní àlààfíà.

16. Báwo ni ẹ̀yin aya ṣe mọ̀ pé ẹ̀yin ni yóò gba ọkọ yín là? Bákan náà ni a lè wí nípa ọkọ tí í ṣe onígbàgbọ́ pé, kò sí ìdánilójú pé aya aláìgbàgbọ́ le yípadà láti di onígbàgbọ́ nípa dídúró ti ọkọ.

17. Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí olúkúlùkù máa gbé ìgbé ayé tí Ọlọ́run ń fẹ́ yín fún, àti nínú èyí tí Olúwa pè é sí. Ìlànà àti òfin mi fún gbogbo ìjọ ni èyi.

18. Ǹjẹ́ ọkùnrin kan há ti kọlà nígbà tí a pè é? Kí ó má sì ṣe di aláìkọlà. Ǹjẹ́ ọkùnrin kan ha ti kọlà nígbà tí a pè é? Kí ó ma ṣe kọlà.

19. Ìkọlà kò jẹ́ nǹkan àti àìkọlà kò jẹ́ nǹkan, bí kò ṣe pípa òfin Ọlọ́run mọ́.

20. Ó yẹ kí ẹnìkọ̀ọ̀kan máa ṣe iṣẹ́ tí ó ń ṣe tẹ́lẹ̀, kí Ọlọ́run tó pé é sínú ìgbàgbọ́ nínú Kírísítì.

21. Ǹjẹ́ ẹrú ni ọ́ bí nígbà ti a pè ọ́? Má ṣe kà á sí. Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá le di òmìnira, kúkú ṣe èyí nì.

22. Tí ó bá jẹ́ ẹrú, ti Olúwa sì pé ọ, rántí pé Kírísítì ti sọ ọ́ di òmìnira kúrò lọ́wọ́ agbára búburú ti ẹ̀ṣẹ̀. Tí ó bá sì ti pé ọ̀ nítòótọ́ tí ó sì ti di òmìnira, ó ti di ẹrú Kírísítì.

23. A sì ti rá yín ní iyè kan, nítorí náà ẹ má ṣe di ẹrú ènìyàn.

24. Ará, jẹ́ kí olúkúlùkù ènìyàn, nínú èyí tí a pè é, kí ó dúró nínú ọ̀kan náà pẹ̀lú Ọlọ́run.

25. Ṣùgbọ́n nípa ti àwọn wúndíá: èmi kò ní aṣẹ kankan láti ọ̀dọ̀ Olúwa, ṣùgbọ́n mo wí fún yín ní ìdájọ́ bí ẹni tí ó rí àánú Olúwa gbà láti jẹ́ olódodo.

26. Nítorí náà mo rò pé èyí dára nítorí wàhálà ìsinsinyìí, èyi nì ni pé o dára fún ènìyàn kí ó wà bí ẹ ṣe wà.

27. Ṣùgbọ́n tí ó bá ti gbéyàwó tàbí tí ó bá ti lákòókó, ẹ má ṣe kọ ara yín sílẹ̀, nítorí èyí tí mo wí yìí. Ṣùgbọ́n tí kò bá sì tí ì gbéyàwó, tàbí fẹ́ ọkọ, má ṣe sáre láti ṣe bẹ́ẹ̀ lákókó yìí.

28. Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá gbé ìyàwó ìwọ kò dẹ́sẹ̀, bí a bá gbé wúndíá ní ìyàwó òun kò dẹ́sẹ̀. Ṣùgbọ́n irú àwọn tí ó bá gbé ìyàwó yóò dojú kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàhálà nípa ti ara: ṣùgbọ́n mo dá a yín sí.

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 7