Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 12:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ti Ẹ̀mí Mímọ́ ẹ̀yin ará, kò yẹ́ kí ẹ jẹ́ òpè.

2. Ẹ̀yin kò mọ̀ pé nígbà tí ẹ̀yin jẹ́ abọ̀rìṣà, a fà yín lọ sọ́dọ̀ odi òrìṣà, ni ọ̀nà tí ó wù kí a gbà fà yín lọ.

3. Nítorí náà, èmí ń sọ fún un yín pé kò sí ẹni ti ń sọ̀rọ̀ nípaṣẹ̀ Ẹ̀mí Ọlọ́run tí ó lè wí pé, “Ẹni ìfibú ni Jésù,” àti pé kò sí ẹni tí ó lè sọ pé, “Olúwa ni Jésù,” bí kò ṣe nípàṣẹ̀ Ẹ̀mí mímọ́.

4. Ǹjẹ́ onírúurú ẹ̀bùn ni ó wà, ùgbọ́n Ẹ̀mí kan náà ni.

5. Onírúurú iṣẹ́-ìranṣẹ́ ni ó sì wà, ṣùgbọ́n Ọlọ́run kan náà sì ni.

6. Onírúurú iṣẹ́-ìranṣẹ́ ni ó sì wà, ṣùgbọ́n lọ́run kan náà ni ẹni tí ń ṣisẹ́ gbogbo wọn níní gbogbo wọn.

7. Ṣùgbọ́n à ń fi ẹ̀bùn Ẹ̀mí fún olúkúlùkù ènìyàn láti fi jèrè.

8. Ẹ̀mí Mímọ́ lè fún ẹnìkan ní ọgbọ́n láti lè fún ènìyàn lámọ́ràn, ẹlòmíràn ní ẹ̀bùn láti sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ìmọ̀ ńlá. Láti ọ̀dọ̀ Ẹ̀mí Mimọ́ kan náà ni èyì ti wá.

9. Ó fi ẹ̀bùn ìgbàgbọ́ fún ẹlòmíràn, ẹlòmíràn ló sì fi agbára ìwonisàn fún nípa Ẹ̀mí Mímọ́ kan náà.

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 12