Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 11:23-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

23. Nítorí èyí tí èmi gbà lọ́wọ́ Olúwa ni mo ti fi fún un yin. Ní alẹ́ ọjọ́ tí Júdásì fi hàn, Olúwa Jésù Kírísítì mú búrẹ́dí.

24. Lẹ́yìn igbà tí ó ti dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run fún àkàrà náà tan, ó bù ú, ó fi fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ gbà kí ẹ sì jẹ, èyí ní ara mi tí a fi fún un yín. Ẹ máa ṣe eléyìí ni rántí mi.”

25. Bákan náà ló mu kọ́ọ̀bù ọtí wáìnì lẹ́yìn oúnjẹ, ó sì wí pé, “Kọ́ọ̀bù yìí ní májẹ̀mú titun nínú ẹ̀jẹ̀ mi, ẹ máa ṣe èyí, nígbàkígbà ti ẹ̀yìn bá ń mu ú, ní ìrántí mi.”

26. Nítorí nígbákùúgbà tí ẹ bá ń jẹ lára àkàrà yìí, tí ẹ sì ǹ mu nínú kọ́ọ̀bù yìí, ni ẹ tún sọ nipa ikú Olúwa. Ẹ máa ṣe eléyìí títí yóò fi padà dé.

27. Nítorí náà tí ẹnikẹ́ni bá jẹ lára àkàrà yìí, tí ẹ sì ń mu nínú kọ́ọ̀bù Olúwa yìí, ní ọ̀nà tí kò bójúmu, yóò jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ sí ara àti ẹ̀jẹ̀ Olúwa.

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 11