Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 10:14-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Nítorí náà, ẹ̀yín olùfẹ́ ọ̀wọ́n, ẹ sá fún ìbọ̀rìṣà.

15. Èmi ń sọ̀rọ̀ sí ọlọ́gbọ́n ènìyàn, ṣe ìdájọ́ fúnra rẹ̀ ohun tí mo sọ.

16. Ago ìbùkún tí a ń súre sí, kì í ha ṣe jíjẹ́ alábàápín ìdàpọ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ Kírísítì bí? Àkàrà tí a bù, kì í ha ṣe jíjẹ́ alábàápín nínú ara Kírísítì bi?

17. Bí ó ti wù kí ènìyàn pọ̀ níbẹ́ tó, gbogbo wa ní ń jẹ lára àkàrà ẹyọkan ṣoṣo náà Eléyìí fi hàn wá pé gbogbo wá jẹ́ ẹ̀yà ara kan.

18. Ẹ wo Ísírẹ́lì nípa ti ara, àwọn tí ń jẹ ohun ẹbọ kò ha se alábàápín pẹpẹ bí?

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 10