Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Jòhánù 2:13-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Èmi ń kọ̀wé sí yín, ẹ̀yin baba,nítorí tí ẹ̀yin tí mọ ẹni tí ó wà ní àtètèkọ́ṣe,Èmi ń kọ̀wé sí yín, ẹ̀yin ọ̀dọ́mọkùnrin,nítorí tí ẹ̀yin ti ṣẹ́gun ẹni ibi náà.Èmi ń kọ̀wé sí yín, ẹ̀yin ọmọdé mi ọ̀wọ́n,nítorí ẹ̀yin ti mọ Baba.

14. Èmi ń kọ̀wé sí yín, ẹ̀yin baba,nítorí ti ẹ̀yin tí mọ ẹni tí o wà ni àtètékọṣe.Èmi ń kọ̀wé sí yín, ẹ̀yin ọ̀dọ́mọkùnrin,nítorí tí ẹ̀yin ni agbára,tí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sì ń gbé nínú yín,tí ẹ sì ṣẹ́gun ẹni ibi náà.

15. Ẹ má ṣe fẹ́ràn ayé tàbí ohunkóhun tí ń bẹ nínú ayé. Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ràn ayé, ìfẹ́ tí Baba kò sí nínú rẹ̀.

16. Nítorí ohun gbogbo tí ń bẹ nínú ayé: ìfẹ́kùfẹ́ ẹni ẹ̀sẹ̀, ìfẹ́kùfẹ́ ti ojú, àti ìgbéraga ti ohun ti ó ní àti ohun tí ó se: kò wá láti ọ̀dọ̀ Baba bí kò ṣe láti ọwọ́ ayé.

17. Ayé sì ń kọjá lọ àti ìfẹ́kùfẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹni tí ó ba ń ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run ni yóò wà títí láéláé.

18. Ẹ̀yin ọmọ mi ọ̀wọ́n, ìgbà ìkẹyìn ni èyí; bí ẹ̀yin sì tí gbọ́ pé Aṣòdìsí-Kírísítì ń bọ̀ wá, àní nísìnsin yìí, púpọ̀ Aṣòdì-sí-Kírísítì ló ń bẹ. Nípa èyí ni àwa fí mọ́ pé ìgbà ìkẹ́yìn ni èyí.

Ka pipe ipin 1 Jòhánù 2