Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sefanáyà 3:9-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. “Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́,nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa,láti fi ọkàn kan sìnín.

10. Láti òkè odò Etiópíà,àwọn olùsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká,yóò mú ọrẹ wá fún mi.

11. Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútìnítorí gbogbo ìsẹ́ni tí ó ti ṣesí mi, nígbà náà ni èmi yóò mukúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn.Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́ní òkè mímọ́ mi.

12. Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútùàti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárin rẹ̀,wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.

13. Àwọn ìyókù Ísírẹ́lì kì yóò hùwàibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké,bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè níẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rù bà wọ́n.”

14. Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Síónì,kígbé sókè, ìwọ Ísírẹ́lì!Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn,ìwọ ọmọbìnrin Jérúsálẹ́mù.

15. Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nìkúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀ta rẹ padà sẹ́yìn. Olúwa, ọba Ísírẹ́lì wà pẹ̀lú rẹ,Ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.

16. Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jérúsálẹ́mù pé,“Má ṣe bẹ̀rù Síónì;má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.

Ka pipe ipin Sefanáyà 3