Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 79:7-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Nítorí wọ́n ti run Jákọ́bùwọ́n sì sọ ibùgbé Rẹ̀ di ahoro

8. Má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa sí wa lọ́rùnjẹ́ kí àánú Rẹ yà kánkán láti bá wa,nítorí ti a Rẹ̀ wá sílẹ̀ gidigidi.

9. Ràn wá lọ́wọ́, Ọlọ́run Olùgbàlà wa,fún ògo orukọ Rẹ;gbà wá kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jìnnítorí orúkọ Rẹ.

10. Àwọn orílẹ̀ èdè yóò sì máa wí pé,“Níbo ni Ọlọ́run wọn wà?”ní ojú wa.Kí a mọ̀ láàrin àwọn orílẹ̀ èdèkí ó sì gbẹ̀san àwọn ẹ̀jẹ̀ ìránṣẹ́ Rẹ̀ tí a tú jáde.

11. Jẹ́ kí ìmí ẹ̀dùn oǹdè náà wá ṣíwájú Rẹ,gẹ́gẹ́ bí títóbi agbára Rẹìwọ ṣe ìtọ́jú àwọn ti a dá lẹ́bí ikú.

Ka pipe ipin Sáàmù 79