Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 40:1-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Mo fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ dúró de Olúwa;ó sì dẹtí sí mi, ó sì gbọ́ ẹkún mi.

2. Ó fà mí yọ gòkèláti inú ihò ìparun,láti inú ẹrẹ̀ pọ̀tọ̀pọ́tọ̀,ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé orí àpáta,ó sì jẹ́ kí ìgbesẹ̀ mi wà láìfòyà.

3. Ó fi orin titun sí mi lẹ́nu,àní orin ìyìn sí Ọlọ́run wa.Ọ̀pọ̀ yóò ríi wọn yóò sì bẹ̀rù,wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀ lé Olúwa.

4. Ayọ̀ ni fún àwọn wọ̀n ọn-nìtí ó fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé wọntí wọn kò sì yípadà sí agbéraga,tàbí àwọn tí ó yapalọ sí ọ̀dọ̀ ọlọ́run mìíràn.

5. Olúwa Ọlọ́run mi, Ọ̀pọ̀lọpọ̀ni àwọn isẹ́ ìyanu tí ìwọ ti ṣe.Àwọn ohun tí ìwọ ti ṣètò sílẹ̀ fún wa;ni ẹnikẹ́ni kò le kà wọ́n fún ọ lẹ́sẹẹsẹtí èmi yóò sì sọ̀rọ̀ wọn,wọn ju ohun tíènìyàn leè kà lọ.

6. Ẹbọ àti ẹran ẹbọ ni ìwọ kò fẹ́,ìwọ ti sí mi ní etí.Ọrẹ ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ni ìwọ kò bèèrè.

7. Nígbà náà ni mo wí pé,“Èmi nìyí;nínú ìwé kíkà nìa kọ ọ nípa temí wí pé.

8. Mo ní inú dídùnláti ṣe ìfẹ́ ẹ̀ Rẹ,ìwọ Ọlọ́run mi;Òfin Rẹ̀ ń bẹ ní àyà mi.”

9. Èmi ti sọ ìròyìn ayọ̀ ti ìgbàlàláàrin àwùjọ ńlá;wòó,èmi kò pa ètè mí mọ́,gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti mọ̀,ìwọ Olúwa.

10. Èmi kò fi ìrànlọ́wọ́ ìgbàlàsin ní àyà mi,èmí ti sọ̀rọ̀ nípa òtítọ́àti ìgbàlà Rẹ̀:èmi kò sì pa ìṣeun ìfẹ́ Rẹ̀àti òtítọ́ Rẹ̀ mọ́kúrò láàrin àwọn ìjọ ńlá.

11. Ìwọ má ṣe,fa àánú Rẹ̀ tí ó rọnúsẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ mi; Olúwajẹ́ kí ìṣeun ìfẹ́ Rẹàti òtítọ́ Rẹkí ó máa pa mí mọ́títí ayérayé.

12. Nítorí pé àìníye ibini ó yí mi káàkiri,ẹ̀ṣẹ̀ mi sì dì mọ́ mi,títí tí èmi kò fi ríran mọ́;wọ́n pọ̀ ju irun orí mi lọ,àti wí pé àyà mí ti kùnà.

Ka pipe ipin Sáàmù 40