Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 31:7-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Èmi yóò yọ̀, inú mi yóò dùn nínú ìfẹ́ ńlá Rẹ,nítorí ìwọ ti rí ìbìnújẹ́ miìwọ ti mọ̀ ọkàn mi nínú ìpọ́njú.

8. Pẹ̀lú ìwọ kò sì fà mi lé àwọn ọ̀tá lọ́wọ́ìwọ ti fi ẹsẹ̀ mi lé ibi àyè ńlá.

9. Ṣàánú fún mi, ìwọ Olúwa, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú;ojú mi fi ìbìnújẹ́ sùn,ọkàn àti ara mi pẹ̀lú.

10. Èmi fi ìbànújẹ́ lo ọjọ́ miàti àwọn ọdún mi pẹ̀lú ìmí ẹ̀dùn;agbára mi ti kùnà nítorí òṣì mi,egungun mi sì ti rún dànù.

11. Èmi di ẹni ẹ̀gàn láàrin àwọn ọ̀tá mi gbogbo,pẹ̀lú pẹ̀lú láàrin àwọn aládùúgbò mi,mo sì di ẹ̀rù fún àwọn ojúlùmọ̀ mi;àwọn tí ó rí mi ní òde ń yẹra fún mi.

12. Èmi ti di ẹni ìgbàgbé kúrò ní ọkàn gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó ti kú;Èmi sì dàbí ohun èlò tí ó ti fọ́.

13. Nítorí mo gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpayà tí ó yí mi ká;tí wọn gbìmọ̀ pọ̀ sí mi,wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí miláti gba ẹ̀mi mi.

14. Ṣùgbọ́n èmí gbẹ́kẹ̀lé ọ, ìwọ OlúwaMo sọ wí pé, “Ìwọ ní Ọlọ́run mi.”

15. Ìgbà mi ń bẹ ní ọwọ́ Rẹ;gbà mí kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá miàti àwọn onínúnibíni.

16. Jẹ́ kí ojú ù Rẹ kí ó tan ìmọ́lẹ̀ sí ìrànṣẹ́ Rẹ lára;Gbà mí nínú ìfẹ́ẹ̀ Rẹ tí ó dúró ṣinṣin.

17. Má ṣe jẹ́ kí á fi mí sínú ìtijú, Olúwa;nítorí pé mo ké pè ọ́;jẹ́ kí ojú kí ó ti ènìyàn búburú;jẹ́ kí wọ́n lọ pẹ̀lú ìdààmú sí isà òkú.

18. Jẹ́ kí àwọn ètè irọ́ kí ó dákẹ́ jẹ́ẹ́pẹ̀lú ìgbéraga àti ìkẹ́gàn.wọ́n sọ̀rọ̀ àfojúdi sí olódodo.

19. Báwo ni títóbi oore Rẹ̀ ti pọ̀ tó,èyí tí ìwọ ti ní ní ìpamọ́ fún àwọn tí ó bẹ̀rù Rẹ,èyí tí ìwọ rọ̀jò Rẹ̀ níwájú àwọn ènìyàntí wọ́n fi ọ́ se ibi ìsádi wọn.

20. Ní abẹ́ ibòji iwájú Rẹ ni ìwọ pa wọ́n mọ́ síkúrò nínú ìdìmọ̀lù àwọn ènìyàn;ní ibùgbé Rẹ o mú wọn kúrò nínú ewukúrò nínú ìjà ahọ́n.

21. Olùbùkún ni Olúwa,nítorí pé ó ti fi àgbà ìyanu ìfẹ́ tí ó ní sí mi hànnígbà tí mo wà ní ìlú tí wọ́n rọ̀gbà yí ká.

22. Èmí ti sọ nínú ìdágìrì mi,“A gé mi kúrò ní ojú Rẹ!”Ṣíbẹ̀ ìwọ́ ti gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi fún àánúnígbà tí mo ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́.

Ka pipe ipin Sáàmù 31