Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 29:2-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Nígbà tí olódodo bá ń gbilẹ̀, àwọn ènìyàn a yọ̀nígbà tí ènìyàn búburú ń ṣàkóso, àwọn ènìyàn ń kórìíra.

3. Ènìyàn tí ó fẹ́ràn ọgbọ́n mú kí baba rẹ̀ láyọ̀ṣùgbọ́n ẹni ti ń bá aṣẹ́wó kẹ́gbẹ́ ba ọrọ̀ ọ rẹ̀ jẹ́

4. Nípa ìdájọ́ òdodo ni ọba fi í mú ìlú tòrò nini,ṣùgbọ́n èyí tí ń ṣojúkòkòrò àbẹ̀tẹ́lẹ̀ fà á lulẹ̀.

5. Ẹnikẹ́ni tí ó bá tan aládúgbò rẹ̀ó ń dẹ àwọ̀n de ẹsẹ̀ ẹ rẹ̀.

6. Ẹ̀ṣẹ̀ ènìyàn ibi ni ó jẹ́ ìdẹkùn rẹ̀ṣùgbọ́n olódodo le è kọrin kí ó sì máa yọ̀.

7. Olódodo ń ṣaápọn nípa ìdájọ́ òtítọ́ fún àwọn tálákà,ṣùgbọ́n kò sí ohun tí ó kan ènìyàn búburú nínú irú rẹ̀.

8. Àwọn Ẹlẹ́yà a máa ru ìlú sókè,ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn máa ń mú ìbínú kúrò.

9. Bí ọlọ́gbọ́n ènìyàn bá lọ sí ilé ẹjọ́ pẹ̀lú aláìgbọ́naláìgbọ́n a máa bínú a sì máa jà, kò sì ní sí àlàáfíà.

10. Àwọn tí ó ń tàjẹ̀ sílẹ̀ kòrí ẹni-dídúró-ṣinṣinwọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa olódodo.

11. Aláìgbọ́n ènìyàn fi gbogbo ẹ̀nú rẹ̀ bínúṣùgbọ́n ọlọgbọ́n ènìyàn a máa kó ìbínú rẹ̀ ní ìjánu.

12. Bí olórí bá fetí sí irọ́,gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ a di ènìyàn búburú lójú rẹ̀.

13. Tálákà ènìyàn àti aninilára jọ ní àbùdá yìí, Olúwa jẹ́ kí ojú àwọn méjèèjì máa ríran.

14. Bí ọba kan bá ń ṣe ìdájọ́ talákà pẹ̀lú òtítọ́ìtẹ́ ìjọba rẹ yóò fìdí múlẹ̀ nígbà gbogbo.

15. Ọ̀pá ìbániwí ń fún ni ní ọgbọ́nṣùgbọ́n ọmọ tí a fi sílẹ̀ fúnra rẹ̀ a dójú ti ìyá rẹ̀.

Ka pipe ipin Òwe 29