Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 27:21-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Iná fún fàdákà iná ìlérú fún wúrà,ṣùgbọ́n a ń dán ènìyàn wò nípa ìyìn tí ó ń gbà.

22. Bí a tilẹ̀ gún aláìgbọ́n nínú odó,fi ọmọ odó gún-un bí èlùbọ́ìwọ kì yóò le è yọ ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ kúrò ní inú rẹ̀.

23. Rí i dájú pé o mọ ipò tí àwọn agbo àgùntàn rẹ wàbojú tó àwọn agbo màlúù rẹ dáradára;

24. nítorí ọrọ̀ kì í pẹ́ lọ títíadé kì í sì í wà lórí títí láéláé.

25. Nígbà tí a bá kó koríko jọ láti orí òkè

26. àwọn àgùntàn yóò pèṣè aṣọ fún ọ,àti ewúrẹ́ yóò pèṣè owó oko.

Ka pipe ipin Òwe 27