Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 27:20-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Kò tẹ́ ikú àti ìparun lọ́rùn ríbẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ni ojú ènìyàn kò rí ìtẹ́lọ́rùn rí.

21. Iná fún fàdákà iná ìlérú fún wúrà,ṣùgbọ́n a ń dán ènìyàn wò nípa ìyìn tí ó ń gbà.

22. Bí a tilẹ̀ gún aláìgbọ́n nínú odó,fi ọmọ odó gún-un bí èlùbọ́ìwọ kì yóò le è yọ ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ kúrò ní inú rẹ̀.

23. Rí i dájú pé o mọ ipò tí àwọn agbo àgùntàn rẹ wàbojú tó àwọn agbo màlúù rẹ dáradára;

24. nítorí ọrọ̀ kì í pẹ́ lọ títíadé kì í sì í wà lórí títí láéláé.

25. Nígbà tí a bá kó koríko jọ láti orí òkè

26. àwọn àgùntàn yóò pèṣè aṣọ fún ọ,àti ewúrẹ́ yóò pèṣè owó oko.

27. Ìwọ yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ mílíkì ewúrẹ́láti bọ́ ọ àti ìdílé rẹàti láti tọ́jú àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ.

Ka pipe ipin Òwe 27