Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 27:13-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Gba aṣọ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àjòjìfi ṣe ẹ̀rí ìdúró bí o bá ṣe onídùúró fún obìnrin oní ìṣekúṣe.

14. Bí ènìyàn kan ń kígbe e ṣúre fún aládùúgbò rẹ ní òwúrọ̀a ó kà á sí bí èpè.

15. Àyà tí ó máa ń jà dàbíọ̀wààrà òjò ní ọjọ́ tí òjò ń rọ̀;

16. dídá a lẹ́kun dàbí ìgbà tí ènìyàn ń dá afẹ́fẹ́ lẹ́kuntàbí bí ẹni tí ó gbá òróró.

17. Bí irin tí ń pọ́n irin múbẹ́ẹ̀ ni ènìyàn kan ń pọ́n ẹlòmíràn mú.

18. Ẹni tí ó tọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ yóò jẹ èṣo rẹ̀ẹni tí ó sì fojú tó ọ̀gá rẹ̀ yóò gba ọlá.

19. Bí omi tí ń ṣe àfihàn ojú, nígbà tí a bá wò óbẹ́ẹ̀ ni ọkàn ènìyàn ń ṣe àfihàn ènìyàn.

20. Kò tẹ́ ikú àti ìparun lọ́rùn ríbẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ni ojú ènìyàn kò rí ìtẹ́lọ́rùn rí.

21. Iná fún fàdákà iná ìlérú fún wúrà,ṣùgbọ́n a ń dán ènìyàn wò nípa ìyìn tí ó ń gbà.

22. Bí a tilẹ̀ gún aláìgbọ́n nínú odó,fi ọmọ odó gún-un bí èlùbọ́ìwọ kì yóò le è yọ ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ kúrò ní inú rẹ̀.

23. Rí i dájú pé o mọ ipò tí àwọn agbo àgùntàn rẹ wàbojú tó àwọn agbo màlúù rẹ dáradára;

24. nítorí ọrọ̀ kì í pẹ́ lọ títíadé kì í sì í wà lórí títí láéláé.

Ka pipe ipin Òwe 27