Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Òwe 24:20-34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. nítorí ẹni ibi kò ní ìrètí ọjọ́ iwájúa ó sì pa fìtílà àwọn ènìyàn búburú kú.

21. Bẹ̀rù Olúwa àti ọba, ọmọ mi,má sì ṣe dara pọ̀ pẹ̀lú àwọn olórí kunkun

22. nítorí àwọn méjèèjì yóò rán ìparun òjijì sórí wọn,ta ni ó sì mọ irú ìyọnu tí wọ́n lè mú wá?

23. Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú tún jẹ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́gbọ́nláti ṣe ojúṣàájú níbi ìdájọ́ kò dára rárá:

24. Ẹnikẹ́ni tí ó wí fún ẹlẹ́bi pé, “Ìwọ lo jàre”àwọn ènìyàn yóò ṣẹ́ èpè fún un àwọn orílẹ̀ èdè yóò sì kọ̀ ọ́.

25. Ṣùgbọ́n yóò dára fún àwọn tí ń dá ẹlẹ́bi lẹ́bi,ọ̀pọ̀ ìbùkún yóò sì wá sórí wọn.

26. Ìdáhùn òtítọ́ó dàbí ìfẹnu-koni-ní-ẹnu.

27. Parí gbogbo iṣẹ́ ajé rẹsì rí i pé oko rẹ ti ṣe dáradára;lẹ́yìn náà kọ́ ilé rẹ.

28. Má ṣe rojọ́ èké mọ́ aládúgbò rẹ láìnídìí,tàbí kí o fi ètè rẹ tannijẹ.

29. Má ṣe wí pé, “Mà á ṣe é fún un gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún mi;Èmi yóò san ohun tí ó ṣe fún mi padà fún un.”

30. Mo kọjá níbi oko ọ̀lẹ,mo kọjá níbi oko aláìgbọ́n ènìyàn;

31. ẹ̀gún ti hù ní ibi gbogbo,koríko ti gba gbogbo oko náà

32. Mo fi ọkàn mi sí nǹkan tí mo kíyèsímo sì kẹ́kọ̀ọ́ lára ohun tí mo rí;

33. oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀,ìkáwọ́ gbera díẹ̀ láti sinmi

34. Òsì yóò sì dé bá ọ bí adigunjalèàti àìní bí olè.

Ka pipe ipin Òwe 24