Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Orin Sólómónì 6:9-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Àdàbà mi, aláìlábàwọ́n mi, ọ̀kan ni,ọ̀kan ṣoṣo ọmọbìnrin ìyá rẹ,ààyò ẹyọkan ṣoṣo ẹni tí ó bí i.Àwọn obìnrin rí i wọ́n pè é ní alábùkún fúnÀwọn ayaba àti àwọn àlè gbé oríyìn fun-un

10. Ta ni èyí tí ó tàn jáde bí i ìràwọ̀ òwúrọ̀,tí ó dára bí òṣùpá, tí ó mọ́lẹ̀ bí òòrùn,tí ó ní ẹ̀rù bí i jagunjagun pẹ̀lú ọ̀págun?

11. Èmi ṣọ̀kalẹ̀ lọ sí ibi ọgbà èso igiláti wo àwọn ẹ̀ka igi tuntun ní àfonífojì,láti rí i bí àjàrà rúwé,tàbí bí pómégíránéètì ti rúdìí.

12. Kí èmi tó mọ̀,àárẹ̀ ọkàn mú mi, mo sì fẹ́ kí ń wà láàárin àwọn ènìyàn mi.

13. Padà wá, padà wá, ìwọ Ṣúlámátì:padà wá, padà wá, kí àwa kí ó lè yọ́ ọ wòÈéṣe tí ẹ̀yin fẹ́ yọ́ Ṣúlámátì wò,bí ẹni pé orin ijo Máhánáímù?

Ka pipe ipin Orin Sólómónì 6