Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Oníwàásù 11:5-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Gẹ́gẹ́ bí ìwọ kò ti ṣe mọ ojú ọ̀nà afẹ́fẹ́tàbí mọ bí ara tí ń dàgbà nínú ikùn ìyáarẹ̀,bẹ́ẹ̀ náà ni ìwọ kò le è ní òye iṣẹ́ Ọlọ́runẹlẹ́dàá ohun-gbogbo.

6. Fún irúgbìn rẹ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù,má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣọ̀lẹ ní àṣálẹ́,nítorí ìwọ kò mọ èyí tí yóò ṣe rerebóyá èyí tàbí ìyẹntàbí àwọn méjèèjì ni yóò ṣe dáradára bákàn náà.

7. Ìmọ́lẹ̀ dùnÓ sì dára fún ojú láti rí oòrùn.

8. Ṣùgbọ́n jẹ́ kí ènìyàn jẹ̀gbádùn gbogbo iye ọdúntí ó le è lò láyéṣùgbọ́n jẹ́ kí ó rántí ọjọ́ òkùnkùnnítorí wọn ó pọ̀Gbogbo ohun tí ó ń bọ̀ asán ni.

9. Jẹ́ kí inú rẹ dùn, ìwọ ọ̀dọ́mọdé ní ìgbà tí o wà ní èwekí o sì jẹ́ kí ọkàn rẹ fún ọ ní ayọ̀ ní ìgbà èwe rẹ.Tẹ̀lé ọ̀nà ọkàn rẹàti ohunkóhun tí ojú rẹ ríṣùgbọ́n mọ̀ dájú pé nípa gbogbo nǹkan wọ̀nyí niỌlọ́run yóò mú ọ wá sí ìdájọ́.

10. Nítorí náà, mú ìjayà kúrò ní ọkàn rẹkí o sì lé ìbànújẹ́ ara rẹ kúrònítorí èwe àti kékeré kò ní ìtumọ̀.

Ka pipe ipin Oníwàásù 11