Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 5:27-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. Ní ẹṣẹ̀ rẹ̀, ó wólẹ̀ó ṣubú; ó dúbúlẹ̀.Ní ẹṣẹ̀ rẹ̀, ó wó lulẹ̀;ní ibi tí ó gbé wólẹ̀ sí, níbẹ̀ náà ni ó ṣubú kú.

28. “Ìyá Ṣísérà yọjú láti ojú fèrèsé,ó sì kígbe, ó kígbe ní ojú fèrèsé ọlọ́nà pé,‘Èése tí kẹ̀kẹ́ ẹsin rẹ fi pẹ́ bẹ́ẹ̀ láti dé?Èéṣe tí ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́ ẹsin rẹ̀ fí dúró lẹ́yìn?’

29. Àwọn amòye obìnrin rẹ̀ dá a lóhùn;àní òun náà pẹ̀lú ti dá ara rẹ̀ lóhùn pé,

30. ‘Wọn kò ha ti rí wọn, wọn kò ha ti pín ìkógun bọ̀ fún olúkálùkù:ọmọbìnrin kan tàbí méjì fún ọkùnrin kan,fún Ṣísérà ìkógun aṣọ aláràbarà,ìkógun aṣọ aláràbarà àti ọlọ́nà,àwọn aṣọ ọlọ́nà iyebíye fún ọrùn mi,gbogbo wọn tí a kó ní ogun?’

31. “Bẹ́ẹ̀ ni kí ó jẹ́ kí gbogbo àwọn ọ̀ta rẹ kí ó ṣègbé Olúwa!Ṣùgbọ́n jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ ọ ràn bí oòrùn.nígbà tí ó bá yọ nínú agbára rẹ̀.”Ilẹ̀ náà sì simi ní ogójì ọdún

Ka pipe ipin Onídájọ́ 5