Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 2:2-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ bá àwọn ènìyàn ilẹ̀ yí dá májẹ̀mú àlàáfíà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò wó pẹpẹ ibi ìsin òrìṣà wọn lulẹ̀.’ Ṣíbẹ̀ ẹ̀yin ṣe àìgbọ́ràn sími. Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí?

3. Ní báyìí, èmi wí fún un yín pé, èmi kì yóò lé àwọn ènìyàn jáde kúrò níwájú yín; ṣùgbọ́n wọn yóò jẹ́ ẹ̀gún ní ìhà yín, àwọn òrìṣà wọn yóò sì jẹ́ ìdánwò fún un yín.”

4. Bí ańgẹ́lì Olúwa sì ti sọ gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn ará Ísírẹ́lì tan, àwọn ènìyàn náà sì gbé ohùn wọn sókè wọ́n sì sunkún kíkorò,

5. wọ́n sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Bókímù (ibi tí àwọn ènìyàn ti sọkún). Wọ́n sì rúbọ sí Olúwa níbẹ̀.

6. Lẹ́yìn tí Jóṣúà ti tú àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì ká, àwọn ẹ̀yà Ísírẹ́lì kọ̀ọ̀kan lọ sí ilẹ̀ tí a fi fún wọn láti lọ gbà á ní ìní wọn.

7. Àwọn ènìyàn náà sin Olúwa ní gbogbo ìgbà ayé Jóṣúà àti ní gbogbo ọjọ́ àwọn àgbààgbà tí ó wà lẹ́yìn ikú rẹ̀ tí wọ́n sì rí gbogbo iṣẹ́ ńlá tí Olúwa ṣe fún Ísírẹ́lì.

8. Jóṣúà ọmọ Núnì ìránṣẹ́ Olúwa kú ní ẹni àádọ́fà ọdún (110).

9. Wọ́n sì sìnkú rẹ̀ sí ààlà ilẹ̀ ìní rẹ̀ ní Tímínátì-Hérésì ní ilẹ̀ òkè Éfúráímù ní àríwá òkè Gásà.

10. Ní ìgbẹ̀yìn, gbogbo ìran náà sì kú; àwọn ìran tí ó tẹ̀lé wọn kò sì sin Olúwa nítorí wọn kò mọ Olúwa bẹ́ẹ̀ ni wọn kò mọ ohun tí Olúwa ṣe fún Ísírẹ́lì.

Ka pipe ipin Onídájọ́ 2