Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 15:10-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Àwọn ọkùnrin Júdà sì bèèrè pé, “Èéṣe tí ẹ fi wá gbógun tì wá?”Ìdáhùn wọn ni pé, “Awá láti mú Sámúsónì ní ìgbékùn, kí a ṣe sí i bí òun ti ṣe sí wa.”

11. Nígbà náà ni ẹgbẹ̀ẹ́dógún (3000) ọkùnrin láti Júdà sọ̀kalẹ̀ lọ sí ihò àpáta nínú àpáta Étamù, wọ́n sì sọ fún Sámúsónì pé, “Kò ti yé ọ pé àwọn Fílístínì ní ń ṣe alákóṣo lórí wa? Kí ni o ṣe sí wa?”Òun sì dáhùn pé, “Ohun tí wọ́n ṣe sí mi ni èmi náà ṣe sí wọn.”

12. Wọ́n wí pé, “Àwa wá láti dè ọ́, kí a sì fi ọ́ lé àwọn Fílístínì lọ́wọ́.”Sámúsónì wí pé, “Ẹ búra fún mi pé, ẹ̀yin kì yóò fúnra yín pa mí.”

13. “Àwá gbà,” ni ìdáhùn wọn. “Àwa yóò kàn dè ọ́, awa yóò sì fi ọ́ lé wọn lọ́wọ́, àwa kì yóò pa ọ́.” Wọ́n sì dé pẹ̀lú okùn túntún méjì, wọ́n sì mú u jáde wá láti ihò àpáta náà.

14. Bí ó ti sún mọ́ Léhì, àwọn Fílístínì ń pariwo bí wọ́n ṣe ń tò bọ̀. Ẹ̀mí Olúwa bà lé e pẹ̀lú agbára. Àwọn okùn ọwọ́ rẹ̀ dàbí òwú tí ó jóná, ìdè ọwọ́ rẹ̀ já kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.

15. Nígbà tí ó rí egungun àgbọ̀n ìṣàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ túntún kan, ó mú un, ó sì fi pa ẹgbẹ̀rún ọkùnrin.

16. Sámúsónì sì wí pé,“Pẹ̀lú egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kanMo sọ wọ́n di òkìtì kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.Pẹ̀lú egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kanMo ti pa ẹgbẹ̀rún ọkùnrin.”

17. Nígbà tí ó dákẹ́ ọ̀rọ̀ ísọ, ó ju egungun àgbọ̀n ìṣàlẹ̀ náà nù, wọ́n sì pe ibẹ̀ ní Ramati-Léhì (ìtúmọ̀ rẹ̀ jẹ́ egungun àgbọ̀n ìṣàlẹ̀ pa).

18. Nítorí tí òǹgbẹ gbẹ ẹ́ gidigidi, ó ké pe Olúwa, wí pé, “Ìwọ ti fún ìránṣẹ́ ní ìṣẹ́gun tí ó tóbi yìí. Ṣé èmi yóò ha kú pẹ̀lú òǹgbẹ, kí èmi sì ṣubú sí ọwọ́ àwọn aláìkọlà ènìyàn?”

19. Nígbà náà ni Ọlọ́run la kòtò ìṣun omi tí ó wà ní Léhì, omi sì tú jáde láti inú rẹ̀. Nígbà tí Sámúsónì mú mi tan, agbára rẹ̀ sì padà, ọkàn sì sọjí, fún ìdí èyí wọ́n pe ìṣun omi náà ni. Ẹni Hákkò rẹ (oríṣun ẹni tí ó pe Ọlọ́run) èyí tí ó sì wà ní Léhì di òní.

20. Sámúsónì ṣe ìdájọ́ Ísírẹ́lì fún ogún ọdún ní àkókò àwọn ará Fílístínì.

Ka pipe ipin Onídájọ́ 15