Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 11:4-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ní àsìkò kan, nígbà tí àwọn ará Ámónì dìde ogun sí àwọn Ísírẹ́lì,

5. Àwọn ìjòyè: aṣíwájú Gílíádì tọ Jẹ́fítà lọ láti pè é wá láti ilẹ̀ Tóbù.

6. Wọ́n wí fún Jẹ́fità wí pé, “Wá kí o sì jẹ́ olórí ogun wa kí a lè kọjú ogun sí àwọn ará Ámónì.”

7. Jẹ́fítà sì dáhùn pé, “Ṣé kì í ṣe pé ẹ kóríra mi tí ẹ sì lé mi kúrò ní ilé baba mi? Kí ló dé tí ẹ fi tọ̀ mí wá báyìí nígbà tí ẹ wà nínú wàhálà?”

8. Àwọn ìjòyè: àgbà Gílíádì dáhùn pé, “Nítorí rẹ̀ ni àwa fi yípadà sí ọ báyìí: tẹ̀lé wa, kí a lè dojú ìjà kọ àwọn ará Ámónì, ìwọ yóò sì jẹ olórí wa àti gbogbo àwa tí ń gbé ní Gílíádì.”

9. Jẹ́fità dáhùn pé, “Bí ẹ̀yin bá mú mi padà láti bá àwọn ará Ámónì jà àti tí Olúwa bá fi wọ́n lé mi lọ́wọ́: ṣe èmi yóò jẹ́ olórí yín nítòótọ́.”

10. Àwọn ìjòyè Gílíádì dáhùn pé, “Àwa fi Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí: àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá wí.”

11. Jẹ́fità sì tẹ̀lé àwọn olóyè Gílíádì lọ, àwọn ènìyàn náà sì fi ṣe olórí àti ọ̀gágun wọn. Jẹ́fità sì tún sọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ti sọ tẹ́lẹ̀ níwájú Olúwa ní Mísípà.

12. Jẹ́fítà sì rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba àwọn ará Ámónì pé, “Kí ni ẹ̀ṣùn tí o ní sí wa láti fi kàn wá tí ìwọ fi dojú ìjà kọ ilẹ̀ wa?”

Ka pipe ipin Onídájọ́ 11