Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Onídájọ́ 11:13-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Ọba àwọn Ámónì dá àwọn oníṣẹ́ Jẹ́fità lóhùn pé, “Nígbà tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jáde ti Éjíbítì wá. Wọ́n gba ilẹ̀ mi láti Ánónì dé Jábókù, àní dé Jọ́dánì, nítorí náà dá wọn padà lọ ní àlàáfíà àti ní pẹ̀lẹ́ kùtù.”

14. Jẹ́fítà sì tún ránṣẹ́ padà sí ọba àwọn ará Ámónì

15. ó sì wí fún un pé:“Báyìí ni Jẹ́fítà wí: àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kò gba ilẹ̀ Móábù tàbí ilẹ̀ àwọn ará Ámónì.

16. Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde kúrò ní Éjíbítì àwọn ọmọ Ísírẹ́lì la ihà kọjá lọ sí ọ̀nà òkun pupa wọ́n sì lọ sí Kádésì.

17. Nígbà náà Ísírẹ́lì rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba Édómù pé, ‘Gbà fún wa láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kọjá,’ ṣùgbọ́n ọba Édómù kò fetí sí wọn. Wọ́n tún ránṣẹ́ sí ọba Móábù bákan náà òun náà kọ̀. Nítorí náà Ísírẹ́lì dúró sí Kádésì.

Ka pipe ipin Onídájọ́ 11