Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ọbadáyà 1:15-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. “Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílélórí gbogbo àwọn aláìkọlà.Bí ìwọ ti se, bẹ́ẹ̀ ni a ó se sí ìwọ náà;ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.

16. Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ se mu lórí òkè mímọ́ miBẹ́ẹ̀ ni gbogbo aláìkọlà yóò máa mu títíWọn yóò mu wọn yóò sì gbémìWọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò wà rí

17. Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè SíónìWọn yóò sì jẹ́ mímọ́àti ilé Jákọ́bù yóò sì ní ìní wọn

18. Ilé Jákọ́bù yóò sì jẹ́ ináàti ilé Jósẹ́fù ọwọ́ ináilé Ísọ̀ yóò jẹ àkékù koríkowọn yóò fi iná sí i,wọn yóò jo run.Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Ísọ̀.”Nítorí Olúwa ti wí i.

19. Àwọn ará Gúsù yóò ni òkè Ísọ̀,àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò niilẹ̀ àwọn ará Fílísítíánì ní ìní.Wọn yóò sì ni oko Éfúráímù àti Samáríà;Bẹ́ńjámínì yóò ní Gílíádì ní ìní.

20. Àwọn ìgbèkùn Ísírẹ́lì tí ó wà níKénánì yóò ni ilẹ̀ títí dé Séréfátì;àwọn ìgbékùn láti Jérúsálẹ́mùtí ó wà ní Séfárádìyóò ni àwọn ìlú Gúsù ní ìní

21. Àwọn olùgbàlà yóò sì gòkè Síónì wáláti jọba lé orí àwọn òkè Ísọ̀.Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.

Ka pipe ipin Ọbadáyà 1