Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 9:2-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. “Mú kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa pa àjọ ìrékọjá mọ́ ní àsìkò rẹ̀.

3. Ẹ ṣe é ní àsìkò rẹ̀ gan-an ní ìdajì ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí ní ìbámu pẹ̀lú àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀.”

4. Mósè sì sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé kí wọ́n máa pa àjọ ìrékọjá mọ́.

5. Wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀ ní ihà Ṣínáì ní ìdajì ọjọ́ kẹ́rìnlá oṣù kìn-ín-ní. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe gbogbo nǹkan gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mósè.

6. Àwọn díẹ̀ nínú wọn kò lè ṣe àjọ Ìrékọjá lọ́jọ́ náà nítorí pé wọ́n di aláìmọ́ nítorí òkú ènìyàn. Nítorí èyí wọ́n wá sọ́dọ̀ Mósè àti Árónì lọ́jọ́ náà.

7. Wọ́n sọ fún Mósè pé, “A di aláìmọ́ nípa òkú ènìyàn, ṣùgbọ́n kí ló dé tí a kò fi ní í le è fi ọrẹ wa fún Olúwa pẹ̀lú àwọn ará Ísírẹ́lì yòókù ní àsìkò tí a ti yàn.”

8. Mósè sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ dúró kí n ba lè mọ ohun tí Olúwa yóò pa láṣẹ nípa yín.”

9. Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mósè pé,

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 9