Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 32:4-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ni ilẹ̀ tí Olúwa ti ṣẹ́gun níwájú àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì tí ó sì dára fún ohun ọ̀sìn, ṣáwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ohun ọ̀sìn.

5. Tí a bá rí ojú rere rẹ,” wọ́n wí, “jẹ́ kí a fi ilẹ̀ yìí fún ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìní. Má se jẹ́kí a rékọjá odò Jọ́dánì.”

6. Mósè sọ fún àwọn ọmọ Gádì àti fún ọmọ Rúbẹ́nì pé, “Ṣé kí àwọn arákùnrin yín lọ sí ogun, kí ẹ̀yin kí ó sì jókó sí bí?

7. Kí ni ó dé tí o fi mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì láti lọ sí ibi ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn?

8. Èyí ni nǹkan tí baba yín ṣe nígbà tí mo rán wọn láti Kadesi-Báníyà láti lọ wo ilẹ̀ náà.

9. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n lọ sí Àfonífojì Ésíkólù tí wọ́n rí ilẹ̀ náà, wọ́n mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì láti wọ ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn.

10. Ìbínú Olúwa sì dìde sí wọn ní ọjọ́ náà, ó sì búra, wí pé:

11. ‘Nítorí wọn kò tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin náà tí ó jẹ́ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó gòkè láti Éjíbítì ni yóò rí ilẹ̀ tí mo pinnu gẹ́gẹ́ bí ìbúra fún Ábúráhámù, fún Ísáákì àti fún Jákọ́bù:

12. kò sí ẹnìkankan àyàfi Kélẹ́bù ọmọ Jéfúnè ti Kénísì àti Jóṣúà ọmọ Núnì, nítorí wọ́n tẹ̀lé Olúwa tọkàntọkàn.’

13. Ìbínú Olúwa ru sí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ó sì mú wọn rìn ní ihà fún ogójì (40) ọdún, títí tí àwọn ìran tí wọ́n ṣe búburú ní ojú rẹ̀ fi lọ.

14. “Níbí ni ẹ̀yin wà, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀, ẹ̀yin dìde ní ipò bàbá yín, ẹ sì jẹ́ kí ìbínú gbígbóná Olúwa ru sí Ísírẹ́lì.

15. Tí ẹ̀yin bá yípadà ní ẹ̀yìn rẹ̀ yóò sì fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí sílẹ̀ ní ihà, ìwọ yóò sì mú-un ṣe ìparun.”

16. Nígbà náà wọ́n wá sí òkè ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, “Àwa yóò fẹ́ láti kọ́ ilé ẹran níhínyìí fún ohun ọ̀sìn wa, àti ìlú fún àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa.

17. Ṣùgbọ́n àwa ṣetán láti dira ogun ṣááju àwọn ọmọ Ísírẹ́lì títí tí a yóò fi mú wọn dé ọ̀dọ̀ wọn lákokò yìí, àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa yóò gbé inú ìlú tí a mọ odi sí fún ìdábòbò wọn lọ́wọ́ olùgbé ilẹ̀ náà.

18. A kì yóò padà sí ilẹ̀ wa láì ṣe pé gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ti gba ogún wọn.

19. A kì yóò gba ogún kankan pẹ̀lú wọn ní òdìkejì Jọ́dánì, nítorí ogún ti wa, ti wá sí ọ̀dọ̀ wa ní ìhà ìlà oòrùn Jọ́dánì.”

20. Nígbà náà ni Mósè sọ fún wọn pé, “Tí ẹ̀yin yóò bá pa ara yín lára, níwájú Olúwa fún ogún.

21. Bí gbogbo yín yóò bá lọ sí Jọ́dánì ní ìhámọ́ra níwájú Olúwa, títí yóò fi lé àwọn ọ̀ta rẹ̀ kúrò níwájú rẹ̀.

22. Tí a ó sì fi ṣe ilẹ̀ náà níwájú Olúwa; ẹ̀yin lè padà tí yóò sì di òmìnira lọ́wọ́ ìdè níwájú Olúwa àti Ísírẹ́lì. Ilẹ̀ yìí yóò sì jẹ́ ti yín níwájú Olúwa.

23. “Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kọ̀ láti ṣe èyí, ẹ̀yin yóò máa dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa; kí ẹ̀yin kí ó sì mọ̀ dájú pé ẹ̀ṣẹ̀ yín yóò fi yín hàn.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 32