Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 26:40-53 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

40. Àwọn ọmọ Bẹ́là ní pasẹ̀ Árídì àti Náámánì nì yí:ti Árádì, ìdílé àwọn ọmọ Árádì;ti Náámánì, ìdílé àwọn ọmọ Náámánì.

41. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Bẹ́ńjámínì; gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; àti àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàáméjìlélógún ó lé ẹgbẹ̀jọ (45,600).

42. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Dánì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:ti Ṣúhámù, ìdílé àwọn ọmọ ṢúhámùWọ̀nyí ni ìdílé Dánì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:

43. Gbogbo ìdílé àwọn ọmọ Ṣúhámù, gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàáméjìlélọ́gbọ̀n ó lé irínwó (64,400).

44. Ti àwọn ọmọ Ásérì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:ti Ímínà, ìdílé àwọn ọmọ Ímínà;ti Íṣífì, ìdílé àwọn ọmọ Íṣífì;ti Béríà, ìdílé àwọn ọmọ Béríà;

45. Ti àwọn ọmọ Béríà:ti Hébérì, ìdílé àwọn ọmọ Hébérì;ti Mákíẹ́lì, ìdílé àwọn ọmọ Mákíẹ́lì.

46. (Orúkọ ọmọ Áṣérì obìnrin nì jẹ́ Ṣérà.)

47. Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Áṣérì gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbéje (53,400).

48. Ti àwọn ọmọ Náfítalì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:ti Jásélì, ìdílé àwọn ọmọ Jásélì:ti Gúnì, ìdílé àwọn ọmọ Gúnì;

49. ti Jésérì, ìdílé àwọn ọmọ Jéṣérì;ti Ṣílémù, ìdílé àwọn ọmọ Ṣilemù.

50. Wọ̀nyí ni ìdílé ti Náfítalì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé egbéje (45,400).

51. Àpapọ̀ iye tí a kà nínú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́, ó lé ẹgbẹ̀sán ó dín àádọ́rin (601,730).

52. Olúwa sọ fún Mósè pé,

53. “Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ jẹ́ pínpín fún wọn gẹ́gẹ́ bí ogún wọn gẹ́gẹ́ bí iye orúkọ wọn

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 26