Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 21:17-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Nígbà náà ni Ísírẹ́lì kọ orin yìí pé:“Sun jáde, ìwọ kànga!Ẹ máa kọrin nípa rẹ̀,

18. Nípa kanga tí àwọn ọmọ aládé gbẹ́,nítorí àwọn ọlọ́lá ènìyàn ni ó gbẹ́ẹ:tí àwọn ọlọ́lá àwọn ènìyàn sì fiọ̀pá aládé àti ọ̀pá oyè wọn gbẹ́.”Nígbà náà wọ́n kúrò láti ihà lọ sí Mátanà,

19. láti Mátanà lọ sí Náhálíẹ́lì, láti Náhálíẹ́lì lọ sí Bámótì,

20. àti láti Bámótì lọ sí àfonífojì ní Móábù níbi tí òkè Písígà, tí ó wà ní òkè ilé omi ti kọjú sí ihà.

21. Ísírẹ́lì rán oníṣẹ́ láti sọ fún Síhónì ọba àwọn ará Ámórì wí pé:

22. “Jẹ́ kí a kọjá ní orílẹ̀ èdè rẹ. A kò ní kọjá sí inú oko pápá tàbí ọgbà tàbí mu omi láti inú kànga. A máa gba òpópónà náà ti ọba títí tí a ó fi la ilẹ̀ rẹ kọjá.”

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 21