Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 17:7-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Mósè sì fi ọ̀pá wọ̀nyí lélẹ̀ níwájú Olúwa nínú àgọ́ ẹ̀rí.

8. Ó sì se ní ọjọ́ kéjì Mósè wọ inú àgọ́ ẹ̀rí lọ, ó sì rí ọ̀pá Árónì, tí ó dúró fún ẹ̀yà Léfì, kì í ṣe wí pé ó hù nìkan Ṣùgbọ́n ó ruwé, ó yọ ìtànná, ó sì so èso jíjẹ.

9. Nígbà náà ni Mósè kó gbogbo àwọn ọ̀pá jáde láti iwájú Olúwa wá fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì. Wọ́n wò wọ́n, ẹnìkọ̀ọ̀kan sì mú ọ̀pá tirẹ̀.

10. Olúwa sọ fún Mósè pé, “Mú ọ̀pá Árónì padà wá ṣíwájú Ẹ̀rí, láti fi pamọ́ gẹ́gẹ́ bí àmìn fún àwọn ọlọ̀tẹ̀. Èyí ó sì mú òpin bá kíkùn sínú wọn sí mi, kí wọn kí ó má baà kú.”

11. Mósè sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa a láṣẹ fún un.

12. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sọ fún Mósè pé, “Àwa yóò kú! A ti sọnù, gbogbo wa ti sọnù!

13. Ẹnikẹ́ni tí ó bá súnmọ́ tabánákù Olúwa yóò kú. Ṣé gbogbo wa ni yóò kú?”

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 17