Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nehemáyà 6:12-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Èmi wòye pé Ọlọ́run kò rán-an, ṣùgbọ́n ó sọ àṣọtẹ́lẹ̀ sí mi nítorí Tòbáyà àti Sáńbálátì ti bẹ̀ẹ́ ní ọ̀wẹ̀.

13. Wọ́n bẹ̀ẹ́ ní ọ̀wẹ̀ láti dẹ́rù bà mí nítorí kí èmi lè dẹ́ṣẹ̀ nípa ṣíṣe èyí, kí wọn lè bà mí lórúkọ jẹ́, kí n sì di ẹni ẹ̀gàn.

14. A! Ọlọ́run mi, rántí Tòbáyà àti Ṣáńbálátì, nítorí ohun tí wọ́n ti ṣe; kí o sì tún rántí Nóádáyà wòlíì obìnrin àti àwọn wòlíì tókù tí wọ́n ń gbérò láti dẹ́rù bà mí.

15. Bẹ́ẹ̀ ni a parí odi náà ní ọjọ́ kẹẹ̀dọ́gbọ̀n oṣù Élúlì (oṣù kẹsán), láàrin ọjọ́ méjìléláàdọ́ta (52).

16. Nígbà tí àwọn ọ̀ta wa gbọ́ èyí, gbogbo àwọn orílẹ̀ èdè tí ó yí wa ká bẹ̀rù jìnnìjìnnì sì mú wọn, nítorí wọ́n wòye pé iṣẹ́ yìí di ṣíṣe pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run wa.

17. Bákan náà, ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọlọ́láa Júdà ń kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ lẹ́tà ránṣẹ́ sí Tòbáyà, èsì láti ọ̀dọ̀ Tòbáyà sì ń wá sí ọ̀dọ̀ wọn.

18. Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Júdà ti mulẹ̀ pẹ̀lú u rẹ̀, nítorí tí ó jẹ́ àna Ṣekenáyà ọmọ Árà (Ṣáńbálátì fẹ́ ọmọ Ṣekenáyà) ọmọ rẹ̀ Jéhóhánánì sì tún fẹ́ ọmọbìnrin Méṣúlámì ọmọ Bérékíyà

Ka pipe ipin Nehemáyà 6