Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nehemáyà 12:5-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Míjámínì, Móádáyà, Bílígà,

6. Ṣémááyà, Jóíáríbù, Jédááyà,

7. Ṣálù, Ámókì, Hílíkíyà, àti Jédáyà.Wọ̀nyí ni olóórí àwọn àlùfáà àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn ní ìgbà ayé e Jéṣúà.

8. Àwọn ọmọ Léfì ni Jéṣúà, Bínúì, Kádímálì, Ṣérébíà, Júdà àti Mátaníyà ẹ̀ni tí òun pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀, ni àkóso orin ìdúpẹ́.

9. Bákíbúkíyà àti Húnì, àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn dúró sí ìdojúkojú wọn nínú ìsìn.

10. Jéṣúà ni baba Jòíákímù, Jòíákímù ni baba Élíáṣíbù, Élíáṣíbù ni baba Jóíádà,

11. Jóíádà ni baba Jònátanì, Jònátanì sì ni baba Jádúà.

12. Ní ìgbé ayé Jòíakímù, wọ̀nyí ni àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn àlùfáà:ti ìdílé Ṣeráiáyà, Méráyà;ti ìdílé Jeremáyà, Hananíyà;

13. ti ìdílé Éṣírà, Mésúlámù;ti ìdílé Ámáráyà, Jéhóhánánì;

14. ti ìdílé Málúkì, Jònátanì;ti ìdílé Ṣékánáyà, Jóṣéfù;

15. ti ìdílé Hárímù, Ádíná;ti ìdílé Mérémótì Hélíkáyì;

16. ti ìdílé Ídò, Ṣekaráyà;ti ìdílé Gínétónì, Mésúlámù;

17. ti ìdílé Ábíjà, Ṣíkírì;ti ìdílé Míníámínì àti ti ìdílé Móádíà, Pílítaì;

18. ti ìdílé Bílígà, Ṣámúyà;ti ìdílé Ṣémáyà, Jéhónátanì;

19. ti ìdílé Jóíáríbù, Máténáyì;ti ìdílé Jédáíáyà, Húsì;

20. ti ìdílé Ṣálù, Káláyì;ti ìdílé Ámókì, Ébérì;

21. ti ìdílé Hílíkíáyà, Háṣábíáyà;ti ìdílé Jédáíáyà, Nétanẹ́lì.

22. Àwọn olóórí ìdílé àwọn ọmọ Léfì ní ìgbà ayé Élíáṣíbù, Jóíádà, Jóhánánì àti Jádúà, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dáríúsì ará a Páṣíà.

23. Àwọn olórí ìdílé láàrin àwọn ọmọ Léfì títí di àkókò Jóhánánì ọmọ Élíáṣíbù ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.

Ka pipe ipin Nehemáyà 12