Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Míkà 1:6-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. “Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaríà bí òkítì lórí pápá,bí ibi ti à ń lò fún gbíngbin àjàrà.Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì.Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀sẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.

7. Gbogbo àwọn ère fífín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹ́ḿpìlì rẹ̀ ni a ó fi iná sun:Èmi yóò sí pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run.Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà,gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”

8. Nítorí èyí, èmi yóò sì sunkún,èmi yóò sì pohùnréré ẹkún:èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ihòòhòÈmi yóò ké bí akátá,èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.

9. Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlewòtán;ó sì ti wá sí Júdà.Ó sì ti dé ẹnu bodè àwọn ènìyàn mi,àní sí Jérúsálẹ́mù.

Ka pipe ipin Míkà 1