Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Míkà 1:11-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ẹ kọjá lọ ni ìhòòhò àti ni ìtìjú,ìwọ tí ó ń gbé ni Sáfírì.Àwọn tí ó ń gbé ni Sáánánìkì yóò sì jáde wá.Bétésélì wà nínú ọ̀fọ̀;A ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.

12. Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Márátì ń retí ire,Ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu bodè Jérúsálẹ́mù.

13. Ìwọ olùgbé Lákísi,dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára.Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀sí àwọn ọmọbìnrin Síónì,nítorí a rí ìré-òfin-kọjá Ísírẹ́lì nínú rẹ̀.

14. Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀fún Mórésétígátì.Àwọn ilé Ákísíbì yóò jẹ́ ẹlẹ̀tàn sí àwọn ọba Ísírẹ́lì.

15. Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Máréṣà.Ẹni tí ó jẹ́ ogo Ísírẹ́lìyóò sì wá sí Ádúlámù.

16. Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára,sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún,nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.

Ka pipe ipin Míkà 1