Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 8:19-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Mósè sì pa àgbò náà, ó sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yí pẹpẹ náà ká.

20. Ó gé àgbò náà sí wẹ́wẹ́, ó sì sun orí àti àwọn ègé àti ọ̀rá rẹ̀.

21. Ó fi omi fọ gbogbo nǹkan inú àti ẹṣẹ̀ rẹ̀, ó sì sun odidi àgbò náà lórí pẹpẹ bí ẹbọ sísun òórùn dídùn, ẹbọ tí a fi iná se sí Olúwa gẹ́gẹ́ bí Olúwa tí pàṣẹ fún Mósè.

22. Ó sì mú àgbò kejì wa, èyí ni àgbò ìfinijoyè àlùfáà, Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì gbọ́wọ́ lé e lórí.

23. Mósè sì pa àgbò náà, ó sì mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀, ó tọ́ ọ sí ètí ọ̀tún Árónì, sórí àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún àti ti ẹṣẹ̀ ọ̀tún rẹ̀.

24. Mósè sì tún mú àwọn ọmọ Árónì wá ṣíwájú, ó sì mú ẹ̀jẹ̀ díẹ̀ ó fi sí etí ọ̀tún wọn, àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún wọn, ó sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ yí pẹpẹ náà ká.

Ka pipe ipin Léfítíkù 8