Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 26:26-45 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. Èmi yóò dá ìpèsè oúnjẹ yín dúró, débi pé: inú àrò kan ni obìnrin mẹ́wàá yóò ti máa ṣe oúnjẹ yín. Òṣùwọ̀n ni wọn yóò fi máa yọ oúnjẹ yín: Ẹ ó jẹ ṣùgbọ́n, ẹ kò ní yó.

27. “ ‘Lẹ́yìn gbogbo èyí, bí ẹ kò bá gbọ́ tèmi, tí ẹ sì lòdì sí mi,

28. Ní ìbínú mi èmi yóò korò sí yín, èmi tìkara mi yóò fìyà jẹ yín ní ìgbà méje nítorí ẹ̀ṣẹ̀ yín.

29. Ebi náà yóò pa yín débi pé ẹ ó máa jẹ ẹran ara àwọn ọmọ yín ọkùnrin, àti àwọn ọmọ yín obìnrin.

30. Èmi yóò wó àwọn pẹpẹ òrìṣà yín, lórí òkè níbi tí ẹ ti ń sìn: Èmi yóò sì kó òkú yín jọ, sórí àwọn òkú òrìṣà yín. Èmi ó sì kóríra yín.

31. Èmi yóò sọ àwọn ìlú yín di ahoro, èmi yóò sì ba àwọn ilé mímọ́ yín jẹ́. Inú mi kì yóò sì dùn sí òórùn ọrẹ yín mọ́.

32. Èmi yóò pa ilẹ̀ yín run débi pé ẹnu yóò ya àwọn ọ̀ta yín tí ó bá gbé ilẹ̀ náà.

33. Èmi yóò mú ogun dé bá yín: Èmi yóò sì fọ́n yín ká gbogbo àwọn ilẹ̀ àjèjì, ilẹ̀ yín yóò sì di ahoro: àwọn ìlú yín ni a ó sì parun.

34. Ilẹ̀ náà yóò ní ìsinmi (tí kò ni lákòókò ìsinmi rẹ̀) fún gbogbo ìgbà tí ẹ fi wà ní ilẹ̀ àjèjì tí ẹ kò fi lò ó. Ìlẹ̀ náà yóò sinmi láti fi dípò ọdún tí ẹ kọ̀ láti fún un.

35. Níwọ̀n ìgbà tí ẹ kò lò ó, ilẹ̀ náà yóò ní ìsinmi tí kò ní lákòókò ìsinmi rẹ̀ lákókò tí ẹ fi ń gbé orí rẹ̀.

36. “ ‘Èmi yóò jẹ́ kí ó burú fún àwọn tí ó wà ní ilẹ̀ ìgbékùn débi pé ìró ewé tí ń mì lásán yóò máa lé wọn sá. Ẹ ó máa sáré bí ìgbà tí wọ́n ń lé yín lójú ogun. Ẹ ó sì subú láìsí ọ̀ta láyìíká yín

37. Wọn yóò máa subú lu ara wọn, bí ẹni tí ń sá fún ogun nígbà tí kò sí ẹni tí ń lé yín. Ẹ̀yin kì yóò sì ní agbára láti dúró níwájú ọ̀ta yín.

38. Ẹ̀yin yóò ṣègbé láàrin àwọn orílẹ̀ èdè abọ̀rìṣà. Ilẹ̀ ọ̀ta yín yóò sì jẹ yín run.

39. Àwọn tí ó ṣẹ́kù nínú yín ni yóò sòfò dànù ní ilẹ̀ ọ̀ta yín torí ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ti àwọn babańlá yín.

40. “ ‘Bí wọ́n bá jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn àti ti babańlá wọn, ìwà ìṣọ̀tẹ̀ wọn àti bí wọ́n ti ṣe lòdì sí mi.

41. Èyí tó mú mi lòdì sí wọn tí mo fi kó wọn lọ sí ilẹ̀ àwọn ọ̀ta wọn. Nígbà tí wọ́n bá rẹ àìkọlà àyà wọn sílẹ̀ tí wọ́n bá sì gba ìbáwí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

42. Nígbà náà ni Èmi yóò rántí májẹ̀mú mi pẹ̀lú Jákọ́bù àti pẹ̀lú Ísáákì àti pẹ̀lú Ábúráhámù: Èmi yóò sì rántí ilẹ̀ náà.

43. Àwọn ènìyàn náà yóò sì fi ilẹ̀ náà sílẹ̀, yóò sì ní ìsinmi rẹ̀ nígbà tí ó bá wà lófò láìsí wọn níbẹ̀. Wọn yóò sì jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn torí pé wọ́n kọ àwọn òfin mi. Wọ́n sì kórira àwọn àṣẹ mi.

44. Pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, nígbà tí wọ́n bá wà nílé àwọn ọ̀ta wọn, èmi kì yóò ta wọ́n nù, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò kóríra wọn pátapáta: èyi tí ó lè mú mi dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn. Èmi ni Ọlọ́run wọn

45. Nítorí wọn, èmi ó rántí májẹ̀mú mi tí mo ti ṣe pẹ̀lú babańlá wọn. Àwọn tí mo mú jáde kúrò ní ilẹ̀ Éjíbítì lójú gbogbo àwọn orílẹ̀ èdè láti jẹ́ Ọlọ́run wọn. Èmi ni Olúwa.’ ”

Ka pipe ipin Léfítíkù 26