Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 13:9-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá ní àrùn awọ ara tí ń ràn yìí ni kí a mú wá sọ́dọ̀ àlùfáà.

10. Kí àlùfáà yẹ̀ ẹ́ wò bí ìwú funfun kan bá wà lára rẹ̀: èyí tí ó ti sọ irun ibẹ̀ di funfun: tí a sì rí ojú egbò níbi ìwú náà.

11. Àrùn ara burúkú gbáà ni èyí, kí àlùfáà jẹ́ kí ó di mímọ̀ pé irú ẹni bẹ́ẹ̀ kò mọ́: kí ó má ṣe ya ẹni náà sọ́tọ̀ fún àyẹ̀wò torí pé aláìmọ́ ni ẹni náà jẹ́ tẹ́lẹ̀.

12. “Bí àrùn náà bá ràn yíká gbogbo awọ ara rẹ̀ tí àlùfáà sì yẹ̀ ẹ́ wò, tí ó rí i pé àrùn náà ti gba gbogbo ara rẹ̀ láti orí títí dé ẹṣẹ̀,

13. àlùfáà yóò yẹ̀ ẹ́ wò, bí àrùn náà bá ti ran gbogbo àwọ̀ ara rẹ̀, kí àlùfáà sọ pé ó di mímọ́, torí pé gbogbo ara ẹni náà ti di funfun, ó ti mọ́.

14. Ṣùgbọ́n bí ẹran ara rẹ̀ bá tún hàn jáde: Óun yóò di àìmọ́.

15. Bí àlùfáà bá ti rí ẹran ara rẹ̀ kan kí ó pè é ni aláìmọ́. Ẹran ara rẹ̀ di àìmọ́ torí pé ó ní àrùn tí ń ràn.

Ka pipe ipin Léfítíkù 13